ỌJỌ́ BURÚKÚ
Bí ohun rere bá sẹlẹ̀
A dàbí eni pé kí ọjọ́ nà má parí
Ṣùgbọ́n kátówí, kátófọ̀
Ọjọ́ ná á kásẹ̀ nílẹ̀
Ẹkú orí ire ànọ́
Ni yó gbẹ̀yìn ọ̀rọ̀ nà
Bí ẹkú ewu ọmọ
Sẹ́ gbẹ̀yìn ẹkú ìrọ́jú
Ṣùgbọ́n bí ohun búburú bá sẹlẹ̀
Ọjọ́ nà ágùn
Bí eni pé kòní parí
Ẹkún á ma pe ẹkún rán nísẹ́
Ìbànújẹ́ á ṣúko sí ọkàn gbogbo ènìyàn
‘Á ó mà se ò’
Ni yó ma wá láti ọtún
‘A ò ní rí irúrẹ̀ mọ̀’
Ni yó ma wá láti òsì
Olúwa
Má se jẹ́ kí ìbànújẹ́ kángun s’ọdọ mi
Bu òróró ìtùnnú sí ọkàn àwọn tí ówà nínú ìbànújẹ́
Kí o si bùkún
Fún àwọn t’ówà nínú ìdàmú
Kí ògo lé ma jẹ́ tìrẹ
Títí ayérayé
A SORROWFUL DAY
On the day of celebration
It seems as if the day should not end
But in a twinkle of an eye
The day is over
But on the day of sorrow
The day becomes longer
And unending
Tears fills the air
As pain pitches its tent
In the heart of all the people
‘O what a pity’
Comes forth from the right
As ‘Take heart’
Comes forth from the left
O God
May sorrow never befall me
Comfort the sorrowful
And bless those who are in pain
So that all glory
May be yours forever
This poem was written in Yoruba, a language of the Nigerian people.
Written and Translated By: Paul Okunola